Ìpínlẹ̀ Èkìtì
Ìpínlẹ̀ Èkìtì | |
---|---|
Nickname(s): | |
![]() Location of Ekiti State in Nigeria | |
Country | ![]() |
Date created | 1 October 1996 |
Capital | Ado Ekiti |
Government | |
• Governor (List) | Kayode Fayemi [1] |
Area | |
• Total | 6,353 km2 (2,453 sq mi) |
Area rank | 31st of 36 |
Population | |
• Estimate (2005) | 2,737,186 |
• Rank | 29th of 36 |
GDP (PPP) | |
• Year | 2007 |
• Total | $2.85 billion[2] |
• Per capita | $1,169[2] |
Time zone | UTC+01 (WAT) |
ISO 3166 code | NG-EK |
Ìpínlẹ̀ Èkìtì jẹ́ Ìpínlè ní apá ìwọ̀ oòrùn Nàíjíríà tí ó jẹ́ dídásílẹ̀ ní ọjọ́ kìíní oṣù ọwàwà,1996 pẹ̀lú àwọn ìpínlẹ̀ tuntun márùn-rún mìíràn látọwọ́ ọ̀gágun Sani Abacha.
Èkìtì ti jẹ́ ìpínlẹ̀ olómìnira kí àwọn òyìnbó tó dé. Èkìtì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìpílẹ̀ Yorùbá ní ibi tí a mọ̀ sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní òní. Àwọn ará Èkìtì jẹ́ àwọn tí a lè tọpasẹ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọmọ Odùduwà, bàbá àti babańlá ìran Yorùbá.[3]
Èrò méjì lówà nípa ìtàn Èkìtì. Àkọ́kọ́ ni èyí tí ó so Èkìtì mọ́ Ilé-Ifẹ̀. Ìtàn náà sọ pé Ọlọ́fin, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Odùduwà tí ó bí ọmọ mẹ́rìndílógún. Nípa pé wọ́n ń wá ilẹ̀ mìíràn láti gbé, wọ́n kúrò ní Ilé-Ifẹ̀ wọ́n sì pọ̀ sókè rajà. Wọ́n gba Iwò- Elérú ní Isarun wọ́n sì ní láti dúró síbì kan tí orúkọ rẹ̀ ńjẹ́ Igbó-Aka tí kò jìnà sí Ile-Oluji.[4]
Ọlọ́fin àti àwọn ará rẹ̀ tẹ̀síwájú nínú ìrìn-àjò wọn, Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ kan tí orúkọ rẹ̀ ńjẹ́ Ọwá-Obòkun (Ọba ilẹ̀ Ijẹṣà) Orangun tí ó jẹ́ ọba Ìlá pinnu láti dúró sí ibi tí à ń pè nih Ìjẹ̀ṣà ní òní àti Igbomina ní ìpínlẹ̀ Osun.[5] Àwọn ọmọ mẹ́rìlá yòókù tẹ̀síwájú nínú ìrìn àjọ̀ wọn, wọ́n sì gúlẹ̀ sí ibi tí a mọ̀ sí Èkìtì ní òní. Wọ́n ṣe àkíyèsi pé òkè pọ̀ ní ibi tí wọ́n tẹ̀dó sí wọ́n sì pe ibẹ̀ ní 'ilẹ̀ olókìtì' èyí tí ó padà di Èkìtì, báyìí ni Èkìtì ṣe gba orúkọ.Àdàkọ:Cn
Èrò kejì nípa orísun Èkìtì ni pé Odùduwà tó jẹ́ babańlá ìran Yorùbá rin ìrìn-àjò lọ sí Ilé-Ifẹ̀, ó ri pé àwọn kan ti tẹ̀dó sí ibẹ̀. Lára àwọn olórí tí ó bá níbẹ̀ ni Agbonniregun, Obatala, Orelure, Obameri, Elesije, Obamirin, Obalejugbe, ká mẹ́*** ba díẹ̀ nínú wọn. Ohun tí ìtàn sọ nipé àwọn àrọ́mọdọ́mọ Agbọnniregun ni wọ́n wà ní Èkìtì, àpẹẹrẹ ni Alara àti Ajero tí wọ́n jẹ́ ọmọ Ifá. Orunmila [Agbonniregun] gan-gan fún ra ẹ̀ gbé púpọ̀ ayé rẹ̀ ní Adó ìdí nìyín tí wọ́n fi máa sọpé 'Adó ni ilé-Ifá' . Àtìgbà náà ni àwọn ará Èkìtì tih wà níbi tí wọ́n wà dì ọ̀ní.[6]
Kò sí ẹni tí ó lè sọ pàtó ìgbà tí àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀, ìdí ni pé ìmọ̀ mọ̀-ọ́-kọ-mọ̀-ó-kọ̀ ò tí ì dé nígbà náà, ohun kan tí ó dájú tádàá ni pé àwọn èèyàn ti ń gbé ní Èkìtì fún ọ̀pọ̀ ọdún. Ìtàn jẹ́ kí a mọ̀ pé àwọn ọba Èkìtì ní ọlá nígbà ayé wọn ní sẹ́ńtúrì kẹtàlá. Àpẹẹrẹ ni Ewi Ata ti Ado-Ekiti ní ọdún.
Gòmìnà ìpínlè Èkìtì nì Biodun Oyebanji
Àwọn àwòrán.
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]-
Arinta water fall
-
Arinta Waterfall
Itokasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Ekiti State, Nigeria Genealogy". FamilySearch Wiki. 2020-04-11. Retrieved 2022-03-22.
- ↑ 2.0 2.1 "C-GIDD (Canback Global Income Distribution Database)". Canback Dangel. Retrieved 2008-08-20.
- ↑ "About Ekiti State" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2021-07-12. Retrieved 2021-07-12.
- ↑ "How The Ara People Of Ekiti Committed Mass Suicide To Avoid Enslavement". Spread.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-03-23. Archived from the original on 2021-07-12. Retrieved 2021-07-12.
- ↑ Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>
tag; no text was provided for refs named:02
- ↑ "Ekiti Kete - Canada". Archived from the original on 2013-07-17. Retrieved 2018-02-14. Unknown parameter
|url-status=
ignored (help)